Loni ni Ọjọ́ a nṣe àjọ̀dún Òrìṣà Ọbalúwaye



kúu déédéé àsikò yìí, ọmọ Oduduwa àtàtà kakiri agbaye

Orúkọ tèmi ni Olukọ̀ Agba Adelson de Brito ti ọpọ eeyan mọ̀ sí Mawo Adelson.

Olori ẹsin ibilẹ̀ Òrìsà àti Vodun ti Afirika ni mi

Olukọ Èdè àti àṣà Yorùba-Ànàgó ni mi.

Ọmọ ọmọ ènìyàn Ànàgó ti wọ́n bi àti dagba ni Ilẹ̀ okeere ni mi.

Àwọn obi mi bi mi ni Ìlú Salvador, Olu-ilu ipinlẹ̀ Baííà, ni orílẹ̀-èdè Burasili.

Mo sọ pẹ̀lú gbogbo yín lati ìlú yìí ni bayìí.

Inu mi dun gan

Ope lowo Eledumare

Gbogbo irunmale ti ile Oduduwa fún mi anfaani yii, lati kopa ni eto yii, po pelo Ojogbon Mateus Aleluya

Ṣe o mọ wipe ni Ìlú mi àwọn aláwọ̀ dúdú pọ̀ júlọ agbaye lẹhin Afirika?

O ee e ti o mo wípè eya Ánàgó jẹ́ àwn ọm Oduduwa ti a ji lati agbegbe ti iwoorun ilẹ̀ aláwo dúdú, nipasẹ àwọn oniṣowo ẹrú lakoko iṣowo ẹrú?

Se o mo wípè Gbogbo ijọsin Ọlọ́run ni imisi Eleduwa ni o si ni ere fún ẹ̀kọ́, fún ajọṣe, fún ikọ́ni ti o wa ninu òdodo?

Bẹẹni, ẹyin ọmọ, kò si Igbagbọ akọkọ ati alailẹgbẹ ati iyasọtọ ti o yori si Ọlọrun.

A tẹle àwọn ọna Òrìṣà àti Vodun

Loni ni jọ́ Aje,

Ni ìlú yìí, ni ọjọ́ Aje a ń bọ Èṣù Ẹlẹ́gbara,

Ni jọ́ Aje, awa tún nbọ Òrìṣà Ọmọolú àbi Ọbalúwaye.

A kò gbọ́dọ̀ gbàbé wípè o yẹ ki a bọ àwọn Èṣù Ẹlẹ́gbara ki a to ki òrìṣà miiran…

Èṣù Láàlú

Ogiri okó

Laroye àroógọ

Abániwọràn báòrídá …

Loni ní ọjọ́ mẹ́rindinlogun, oṣù kẹ̀jọ ọdún.

Loni di gẹgẹ bi ọjọ́ ti o pàtàkì jù laarin gbogbo ọjọ́ Aje miran lọ, nitori oni ni ọjọ́ lọdọọdun ajọdún òrìṣà Ọbaluwaye.

balúwaiyé tabi “ba ti Olú Aye” jẹ́ ọ̀à kan tí awa ń b ni jọ́ Aje lìlú wa.

Awa tún a n pè òrìṣà yìí molú...

e o mọ̀ itúmọ̀ molú...?

molú túmọ̀ si “m ti ba” tabi “m ba”. ùgbọ́n, àwn olórìà gbàgbọ́ pé Ó mọ̀ Omolú nitori “Olú” ni orúkọ Ìyá rẹ̀.

Ninu Ẹsin ibilẹ̀ Nàgó-Vodun ni ìlú wa, wn pè Òrìá yìí “Vodun Azonsù” ti túmọ̀ ni “Òrìà ti kunrin aláìsàn” ni èdè Fon tabi  “Fɔngbè ...

Fɔngbè jẹ́ èdè ti àwọn ọm ẹ̀yà Fon lò ni atijọ́ ijba Dahomey ni igba laelae ni ìwọ̀-oòrùn ilẹ̀ Afrika.  

Àwn agbalagba s nipa balúwayé pe ènìyàn ni ie.

Wn ni Òrìa yìí d´àgba gidigidi, o si d´árúgbó to bẹẹ ti kò le fi ẹsẹ̀ mejeeji rin pẹ̀lú agbára m.

Fún idi eyi, igi ni Ó fi ne ẹketa ẹsẹ rẹ̀.

Nitori ó d´árúgbó pupo ti o fẹran si duro ni ibi si ipalọlọ, àwọn onigbagbọ ni “atóto” ń balúwayé.

Ó ni agbára gidi lori ibà ati lodi si gbogbo àwọn arun, ni pàtàkì si àwọn arun awọ-ara, àwn igbona, ati àwọn arun afẹfẹ ti o le fa ajakálẹ̀ arun.

balúwayé ṣe iwosan àwọn ènìyàn ti o ni àwọn iṣoro ijagba, ìwárapa ati àwn arun ẹ̀gbà.

Ó korira àwọn ibi ti oju otutu.

Eyikeyi iru ẹbọ tabi gbadura si Ọbalúwayé gbọdọ ṣe lakoko ọjọ́, kì í i ṣe ni alẹ̀ nigba ti otutu ti l silẹ̀.

balúwaiyé tabi “ba ti Olú Aye” jẹ́ ọ̀à kan tí awa ń b ni jọ́ Aje lìlú wa.

Oun ni oluwa ilẹ ti o gba àwọn ara eeyan lẹhin ti wọ́n jade laye.

Jẹ́ ki gbogbo ọmọ Eleduwa ronu gidi pè, laarin igbesi aye wa, lojoojumọ, diẹ diẹ, téré, a ń lọ si ọdọ ijọba Bàbá Onilẹ̀...je ki a n korin…

 Ẹrú ìyá, ẹrú ìyá o,

Bàbá sàree ìlú jìyà, a gbọ́dọ̀ téré (Olukorin)

Oniye ara aye

Ẹrú jiya, ẹrú jiya o

Bàbá sàree ìlú jìyà ( Olulorin)

Reference:

1. Image: https://www.picfair.com/pics/06020031-benin-west-africa-porto-novo-zangbeto-guardian-of-the-night-spirit-dance (16/08/21) 

Comentários

Postagens mais visitadas deste blog

Ẹ kaabọ̀ si Kilombo Kingoma náà, akọkọ ilẹ̀ ibilẹ̀ Afirika ni okeere

Ìtàn òrìṣà Ṣàngó ti a ranti nínú ìjọsìn wa apa keji

Ògún Lakaye Osìn imọlẹ̀