Ọjọ́ oni ni Ọjọ́ Abámẹ́ta





Ẹ kú dédé àsìkò yìí gbogbo olólùfẹ́ èdè àti àsà Ànàgó

Mo ki gbogbo yin!

Ọjọ́ oni ni Ọjọ́ Abámẹ́ta, Ọjọ́ kejìdínlógún, oṣù kejìlá ọdún, abi,

gẹ́gẹ́ bí Kalẹ́ńdà ibilẹ̀ Yorùbá ṣe sọ, Ọjọ́ kejìdínlógún Ọpẹ́.

Awa ń tẹsiwaju bọ àwọn irunmọnlẹ̀, òrìṣà ati vodun ti àwọn alálẹ̀ wa mu wa láti ila oorun ilẹ̀ aláwọ̀ dúdú ni ìgbà atijọ, laarin èto òwò ẹrú agbaye.

Mo ń gbé ni ìlú Salvador, olú-ìlú iipinlẹ Baííà ni orílẹ̀-èdè Brasili, tíi ṣé orílẹ̀-èdè keji ti àwọn aláwọ̀ dúdú pọ̀ si jùlọ agbaye lẹhin Naijiria.

 Ní ìlú Salvador lọjọ́ oni, àwọn onígbàgbọ́ orìṣà àti Vodun ń bọ àwon òrìṣà ati Vodun ti daabo àwọn ojà bo.

Orúkọ temi ni Olukọ Agba Adelson de Brito ti ọ̀pọ̀ eeyan mọ̀ si Mawo Adelson.

Mo si tún jẹ́ olori ilé-ijọsin ibilẹ̀ Òrìṣà ati Vodun ti orúkọ̀ rẹ̀ ni Hunkpamẹ Savalou Ànàgo-Vodun Sakpata-Azonsu nu Xwe ti o wa ni ìlú Arembepe tabi ìlú Arẹ̀ańgbépẹ ìlú ti o di pàtàkì fún ìtan àwọn ọmọ dúdú ni ipinlẹ̀ Baííà

Tẹ́ẹ bá fẹ́ gba àdúrà sì àwọn òrìṣà ilẹ̀ Oduduwa, ẹ jẹ́ ki ẹẹ́ lo èdè abinibi àwon bàbá nla wa.

Lati igba ewe mi ti mo ń bọ latẹnu àwọn àgbalagbà pe o ṣe pàtàkì ki ẹẹ́ lo èdè Ànàgó láti gbadura sì àwọn òrìṣà ati irumọlẹ̀ ati Vodun ilẹ̀ atilẹba àwon alálẹ̀ wa.

Lode oni wọ́n pe èdè Ànàgó bi èdè Yorùbá.

Lati aye atijọ́ ni Yorùbá ti ni ìgbàgbọ́ ninu ki a gba àdúrà nitori pe ohun gbogbo fẹ́ àdúrà “Ohun ti o dára fẹ́ àdúrà ki ó bà lé dára si, eyi ti kò dára na fẹ́ àdúrà ki ó bà lé yanjú”

A kò gbọdọ gbagbe pe lakọkọ ni ẹẹ́ jẹ́ ki ń bọ Eṣù Ẹlẹ́gbara.

Jẹ́ ki a sọ:

Kò gbá, Laroye Eṣù

Eṣù kì í ṣùsù ọ̀na

Kò gbá, Laroye

Ago mojúbà Eṣu

Eṣu mojúbà

Ẹlẹ́gbara ajágbọn wo sì

Araketu ń sọ̀rọ̀ ṣòrò

Eṣu jinni jinni

Kò gbá, Laroye

Jẹ́ ki a gbadura si àwon Vodun Avesan ati òrìṣà Ọya àti gbogbo irunmọlẹ̀ Ìyagba ọrún fún wa ounje wa tiwa ni ọjọ́ oni ati lojoojumọ laarin ọdún to ń bọ.

Aṣẹ!

Comentários