Postagens

Ẹ kaabọ̀ si Kilombo Kingoma náà, akọkọ ilẹ̀ ibilẹ̀ Afirika ni okeere

Imagem
  Ìlú wo lo gb ọ Yorùbá jùl ọ ni oríl ẹ̀ èdè Brasil? Ìlú náà ti ọ̀pọ̀ ènìyàn ń pé ní ìlú Bahia. Orúkọ̀ mi ni Adelson Adewale de Brito ti ọpọlọpọ ènìyàn mọ̀ si Ọ̀mọ̀wé Adelson tabi Mọ̀wé Adelson tabi Mawo Adelson. Mo ki gbogbo ilé, Mo ki awon baba nla wá, Mo ki, awon Ìyá nlá wa. Oduduwa Mo juba! Mo ki awon omo iya fún ajoyo yìí. Mo b ẹ È ṣ ù Ẹ l ẹ́ gbára, ki ó fún wa ni ọ̀ na ti o dará, ti o si ye kooro. Jẹ́ ki a ki Èṣù ni ṣaaju ki a sọ̀rọ̀ nipa ohunkohun ninu èto wa loni: Ago, Mo júbà Èṣù,Èṣù, Mo júbà Mo ki Ẹlẹ́gbára ti won ri ajagbọn wa ti o farasin Araketu náà ti o ń sọ̀rọ̀ ń sọ̀rọ̀ Èṣù jinnijinni Kò gba Laroye! Ni ọjọ́ m ọ kandinlogun o ṣ ù Ẹrẹ́nà yìí   lára abẹwo ìgbà keji si orílẹ̀-èdè Brasil, Ọọ̀ni Ile-Ifẹ náà, Ọba Adeyẹye Ogunwusi Ọjaja keji wa si ìlú Lauro de Freitas ni ipinl ẹ̀ Bahia lati s ọ̀ Kilombo Kingoma náà lel ẹ̀ g ẹg ẹ bi ak ọkọ il ẹ̀ ibil ẹ̀ Afirika ni okeere. Ni oruko temi ati loruko gbogbo ọmọ  ìlú Lauro de Freita...

Ijàgbara àwọn ìmale

Imagem
  Iṣẹlẹ iyalẹnu kan ti o ṣẹlẹ ni òwúr ọ̀ ọjọ́ k ẹ ẹdọ́gbọn o ṣù Kinni,Ọdún 1835, ni Ìlú Salvador, olu ìlú ìpinl ẹ̀ Bahia. Ìwà Àìní-ìtẹ́ l ọ́rùn, ìrẹ́jẹ ati aisi idajọ̀ ododo lori òwò ẹrú ń pọ̀ síí lójoojúmọ́.   Ni ọjọ́ ta wi yìí, ẹgb ẹ́ta ẹrú kó ori ṣiriṣi ohun ija l ọ si ita gbangba lati ja lori ọ̀rọ̀ òwò ẹrú. Wọn pinnu lati fi opin si èto buruku y ẹ n ti kò ka wọn si ènìyàn.   Iṣẹlẹ náà j ẹ́ ijagbára to lokiki jùl ọ ni gbogbo ìpinl ẹ̀ Bahia. Nitori pe púp ọ̀ ninu àwọn ẹrú ti o kopa ninu ìjàgb á ra náà j ẹ́ musulumi, a n pe orúkọ r ẹ̀ ni “ Ìjàgbara àwọn Ìmale” tabi Ìjà àwọn ìmale .   “Ìmale” ni orúkọ ti wọn n pe à wọn ẹl ẹ́ sin musulumi ni èdè Ànàgó (tabi èdèYorùbá).   Àwọn ọmọ il ẹ̀ Aláwọ̀ dúdú nikan lo jà ijà náà. Àwọn ẹrú ti a bi ni Ìlú Brasili, ti a pe ni “ àwọn   Kreoles ”, kò l ọ w ọ́ si . 

Ẹ kaabọ̀ si ìlú Salvador, Ojogbọ́n Babalawo Ogundeji Ifadamitan Elebuibon!

Imagem
  Mo ki eyin baba mi, mo ki eyin Ìyá mi. Mo ki eyin Ẹgbọn mi ati aburo mi fún ayeye ọdún yìí. Mo b ẹ È ṣ ù Ẹ l ẹ́ gbára,ki ó fún wa ni ọ̀ na ti o dará, ti o si ye kooro. Jẹ́ ki a ki Èṣù ni ṣaaju ki a sọ̀rọ̀ nipa ohunkohun ninu èto wa loni:   Ago, Mo júbà Èṣù Èṣù, Mo júbà Ẹlẹ́gbára ri ajagbọn wa ti o farasin   Araketu náà ti o ń sọ̀rọ̀ ń sọ̀rọ̀ Èṣù jinnijinni Kò gba Laroye!   Mo dúpẹ́ Oluwo Awoosore Ifdamitan Daniel Diniz ti wọn ń pe mi lati kopa ninu ipade yìí.   Emi ni ọmọ Oduduwa. Mo ki yin ọmọ ìyá mi kaakiri àwọn orílẹ̀èdè lagbaye Ẹ ku ọdún tuntun!   Orúkọ̀ mi ni Adelson Adewale de Brito ti ọpọlọpọ ènìyàn mọ̀ si Ọ̀mọ̀wé Adelson tabi Mọ̀wé Adelson tabi Mawo Adelson. Mo ki gbogbo ilé, Ẹ kaasan! Mo ki dọ́kità Ogundeji Ifadamitan Elebuibon Ẹ kaabọ̀ Ojogbọ́n! Mo ki yin Ẹ káàbọ̀ pẹ̀lu inudidun pe Mo lo èdè àwọn Bàbá nlá wa lati ki yin “Ẹ́ káàbọ̀” si ìlú Salvador, Olu-ìlú ipinlẹ̀ Baííà. Ìlú Salvador jẹ́ ìl...

Ìtàn òrìṣà Ṣàngó ti a ranti nínú ìjọsìn wa apa keji

Imagem
  Gẹgẹbi ọba, ó lágbára gan o si ni igboyà, ó máa lọ ko ijà kaakiri agbegbe yẹn. Ó fẹ́ràn lati maa fi agbára rẹ̀ han àwọn ènìyàn. Ìtàn sọ fún wa pé ni igba kan, Ṣàngó lo da ìjà silẹ̀ láàárín àwọn ìjòyè meji kan ni ìlú rẹ̀. Ikórìíra dá dá dá sí í pọ̀ débi pé ọ̀kan pa èkeji. Ọ̀pọlọ́pọ̀ àwọn olugbe Ọ̀yọ ri ohun buburu ti ọba náà ti ṣe lori àwọn ọkunrin meji yìí. Nitori idi eyi wọ́n dide ọ̀tẹ̀ si aláde. Iye eeiyan ti alaifẹ́ si ọ̀ba náà dagba gidi gan an to fa rúdurùdu wa ti mbẹ ni ìlú Ọ̀yọ. Nikẹhin, Ṣàngó ri agbára iṣelu ijọba tirẹ̀ padanu patapata mọ. Koda ó kò ri ilé duro tabi ri ènìyàn lati tù u ninu. Itan sọ fún wa pé Ṣàngó ro´nu ara rẹ̀ gan titi kò ri ohun kankan ti o le ṣe lati yanju ipo rẹ̀, ó wa yà sì ìdí igi àyàn kan. Ọba náà pokunso. Ibi naa eiyití ẹmí Sàngó kuro ninu ilé aye lati lọ sì ọ̀dọ̀ Oduduwa, o wà nítòsí ìlú kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kosò, ti o wa kò jinna si Ọ̀yọ. Lati igba náà ni àwọn ọ̀tá Ṣàngó sì wípè “Ọba sọ” l...

Ògún Lakaye Osìn imọlẹ̀

Imagem
Ẹ ku deedee asiko yìí eyin ọmọ Ànàgó atata ! Ṣe alaafia ni? Ọjọ́ oni ni ọjọ́ ì ṣẹ́ gun ni ilẹ̀ àwa ọmọ Yoruba atata, Ní  ọjọ́ ìṣẹ́gun a ń b ọ́ Òrìṣà Ògún Ògún yè, pàtàkì ori Láàárin gbogbo iranṣe Olodumare! Orúkọ̀ temi ni Olukọ Agba Adelson de Brito ti ọ̀pọ̀ eeyan mọ̀ sì Mawo Adelson. Ọmọ ẹya Ànàgó ni mi,   ọmọ Oduduwa ni mi. Mo ki gbogbo ọmo ìyá Yorùbá kaakiri agbaye. Ògún ni òrìṣà ìbílẹ̀ ti daabo àwọn jagunjagun, àwọn ọdẹ, àwọn alágbẹ̀dẹ , àwọn onímọ̀ ẹ̀rọ, àti àwọn awakọ̀ ní ẹkùn ilẹ̀ Yorùbá. Àwọn ọmọlẹ́yìn ẹ̀sìn ìbílẹ̀ Yorùbá lè búra láti sọ òtítọ́ ní ilé ẹjọ́ nípa “fi ẹnu kò irin kan ní orúkọ Ògún.” Àwon awakọ̀ gbe amuleto Ògún lati dena ijamba ọkọ̀.  Ní ìlú wa lode oni a n bọ Ògún ni olúkúlùkù ilé ẹ̀sìn ìbílẹ̀ òrìṣà ti a ń pé ni Kandọnbilẹ́ (Candomblé). Mo tún j ẹ́ olori ẹsin ibilẹ̀ vodun kan lati il ẹ̀ ij ọba atij ọ́ Dahomy ti a ń pé ni Jeje. Ninu ẹsin Dahomey yìí, Gu ni vodun ti ogun ati ọlọrun alabojuto ti àwọn alagbẹdẹ ati à...

Ìtàn òrìṣà Ṣàngó ti a ranti nínú ìjọsìn wa apa kini

Imagem
  Ni ode oni, wọ́n ń sin àwọn òrìṣà Oduduwa lágbàáyé, paapaa ni àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ Af´rika bii Nàìjíríà, Bẹnin ati, Togo, bẹ́ẹ̀ ni lára àwọn orílẹ̀-èdè mii, bii Amẹrika, Kuba, Brasili ati àwọn ìlẹ̀ kaakiri Erèkúsú Karibian. Àwọn onigbagbọ ni àwọn òrìṣà wọ̀nyí gẹgẹ bi Ọlọ́run tiwọn. Lara Òrìṣà náà a ni Èṣù, Ogun, Ọbàtálá, Yemọja, Ọ̀ṣun, ati Ṣàngó. Ó ṣeni láàánú pé àwọn Ànàgó (àwọn Yorùbá tó wà ní Brasili) ti ode oni kò lè kẹ́kọ̀ọ́ ìtàn igbesiaye àwọn èèyàn tó di òrìṣà wọ̀nyí latọwọ́ àwọn baba ńlá wa lèdè abibnibi wa. Nitori ipó aiṣe deede wọ́n làwujọ́ ti ilẹ̀ yìí lakoko èto ẹrú, wọ́n kò le ṣeto àwọn ilé-ìwé lati kọ àwọn ọmọ ati iran wọn ni èdè Ànàgó gẹgẹbi èdè ti wọ́n le lo ninu ohun lojoojumọ wọn. Síbẹ̀síbẹ̀, nitori iṣẹ́ takuntakun ti àwọn olori ijọsin òrìṣà ni aye atijọ́ wọ́n lr ipamọ àwọn orin ati àwon gbólóhùn ọ̀rọ̀ atilẹba àwọn wa, a ń tẹsiwaju lo àwọn ilana ijọsin abinibi òrìṣà lati ìgbà òwò ẹrú titi ode oni.  Àwa, ọmọ  Ànà...

Oni ni ajọdún ti Ọọni Ilé-Ifẹ̀ náá ikede ìlú Bahia gẹgẹbi Olú-ìlú Yorùbá ti gbogbo àwọn Amẹ́rikà

Imagem
  Lára abẹwo si orílẹ̀-èdè Brasíìlì ni o ṣù keje, ọdún 2018, Ọọni ile-Ifẹ náà, Ọba Adeyẹye Ogunwusi Ọjaja keji ni: “... àwọn ọmọ Yorùbá to wa kaakiri igun mẹrẹrin agbaye ko gbọdọ sọ ami idanimọ wọn nu, nitori ọmọ iya kan naa ni gbogbo awọn ọmọ Oodua bii Itsekiri, Edo, Ga, Anago, Igala, Lucumi, Tapa, ati Yoruba ti orisun wọn si wa ni ilu Ile Ifẹ...” Àwọn iran ti àwọn Ànàgó ni ode oni ìlú Brasílì kò le lo èdè náà fún àwọn ohun iṣe ti ojojumọ wọn. Sibẹsibẹ, àwọn orin, ijó, ìtan aye atijọ́, ounjẹ ati ẹ̀sin ń ṣiṣe ni ọpọ àgbègbé kaakiri orílẹ̀-èdè náà.   “... àwọn ọmọ Yorùbá to wa kaakiri igun mẹrẹrin agbaye ko gbọdọ sọ ami idanimọ wọn nu, nitori ọmọ iya kan naa ni gbogbo awọn ọmọ Oodua bii Itsekiri, Edo, Ga, Anago, Igala, Lucumi, Tapa, ati Yoruba ti orisun wọn si wa ni ilu Ile Ifẹ...” Àwọn iran ti àwọn Ànàgó ni ode oni ìlú Brasílì kò le lo èdè náà fún àwọn ohun iṣe ti ojojumọ wọn. Sibẹsibẹ, àwọn orin, ijó, ìtan aye atijọ́, ounjẹ ati ẹ̀sin ń ṣiṣe ni ọpọ àgbègbé kaak...